4. Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubẹni, ó rán Ṣamua ọmọ Sakuri;
5. láti inú ẹ̀yà Simeoni, ó rán Ṣafati ọmọ Hori;
6. láti inú ẹ̀yà Juda, ó rán Kalebu, ọmọ Jefune;
7. láti inú ẹ̀yà Isakari, ó rán Igali, ọmọ Josẹfu;
8. láti inú ẹ̀yà Efuraimu, ó rán Hoṣea ọmọ Nuni;
9. láti inú ẹ̀yà Bẹnjamini, ó rán Paliti, ọmọ Rafu;
10. láti inú ẹ̀yà Sebuluni, ó rán Gadieli, ọmọ Sodi;
11. láti inú ẹ̀yà Josẹfu, tí í ṣe ẹ̀yà Manase, ó rán Gadi, ọmọ Susi;
12. láti inú ẹ̀yà Dani, ó rán Amieli, ọmọ Gemali;
13. láti inú ẹ̀yà Aṣeri, ó rán Seturu, ọmọ Mikaeli;
14. láti inú ẹ̀yà Nafutali, ó rán Nahibi ọmọ Fofisi;
15. láti inú ẹ̀yà Gadi, ó rán Geueli ọmọ Maki.
16. Orúkọ àwọn ọkunrin tí Mose rán láti lọ ṣe amí ilẹ̀ náà nìyí. Mose sì yí orúkọ Hoṣea ọmọ Nuni pada sí Joṣua.
17. Mose rán wọn láti lọ ṣe amí ilẹ̀ náà. Kí wọ́n tó lọ, ó sọ fún wọn pé, “Ẹ gba ọ̀nà ìhà àríwá, kí ẹ tọ̀ ọ́ lọ sí ìhà gúsù ilẹ̀ Kenaani, kí ẹ wá lọ sí àwọn orí òkè.