Nọmba 10:22-28 BIBELI MIMỌ (BM)

22. Lẹ́yìn náà ni àwọn tí wọ́n wà lábẹ́ ọ̀págun ẹ̀yà Efuraimu ṣí, wọ́n tò ní ìsọ̀rí-ìsọ̀rí. Eliṣama ọmọ Amihudu ni olórí wọn.

23. Gamalieli ọmọ Pedasuri ni olórí ẹ̀yà Manase.

24. Olórí ẹ̀yà Bẹnjamini sì ni Abidani ọmọ Gideoni.

25. Ní ìparí, àwọn ẹ̀yà tí wọ́n wà lábẹ́ ọ̀págun Dani ṣí, wọ́n tò ní ìsọ̀rí-ìsọ̀rí. Ahieseri ọmọ Amiṣadai ni olórí wọn.

26. Pagieli ọmọ Okirani ni olórí ẹ̀yà Aṣeri.

27. Olórí ẹ̀yà Nafutali sì ni Ahira ọmọ Enani.

28. Bẹ́ẹ̀ ni ètò ìrìn àjò àwọn ọmọ Israẹli rí nígbà tí wọ́n ṣí kúrò ní ibùdó wọn.

Nọmba 10