Nahumu 1:9-13 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Èrò ibi wo ni ẹ̀ ń gbà sí OLUWA?Yóo wulẹ̀ pa yín run patapata ni;kò sì sí ẹni tí OLUWA yóo gbẹ̀san lára rẹ̀ lẹ́ẹ̀kantí yóo lè ṣẹ̀ ẹ́ lẹẹkeji.

10. Wọn yóo jóná bí igbó ẹlẹ́gùn-ún tí ó dí,àní bíi koríko gbígbẹ.

11. Ṣebí ọ̀kan ninu yín ni ó ń gbìmọ̀ burúkú sí OLUWA, tí ó sì ń fúnni ní ìmọ̀ràn burúkú?

12. OLUWA wí pé: “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ará Siria lágbára, tí wọ́n sì pọ̀, a óo pa wọ́n run, wọn yóo sì parẹ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti jẹ ẹ̀yin ọmọ Juda níyà tẹ́lẹ̀, n kò ní jẹ yín níyà mọ́.

13. N óo bọ́ àjàgà Asiria kúrò lọ́rùn yín, n óo sì já ìdè yín.”

Nahumu 1