Matiu 6:9-14 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Nítorí náà, báyìí ni kí ẹ̀yin máa gbadura:‘Baba wa tí ń bẹ ní ọ̀run:Kí á bọ̀wọ̀ fún orúkọ mímọ́ rẹ,

10. kí ìjọba rẹ dé,ìfẹ́ tìrẹ ni kí á ṣe ní ayébí wọ́n ti ń ṣe ní ọ̀run.

11. Fún wa ní oúnjẹ òòjọ́ wa lónìí.

12. Dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wágẹ́gẹ́ bí àwa náà ti dárí ji àwọn tí wọ́n ṣẹ̀ wá.

13. Má fà wá sinu ìdánwò,ṣugbọn gbà wá lọ́wọ́ èṣù.’

14. “Nítorí bí ẹ bá dárí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn eniyan jì wọ́n, Baba yín tí ń bẹ ní ọ̀run yóo dáríjì yín.

Matiu 6