11. Lẹ́yìn náà, Èṣù fi í sílẹ̀. Àwọn angẹli bá wá sọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n ń ṣe iranṣẹ fún un.
12. Nígbà tí Jesu gbọ́ pé wọ́n ti ju Johanu sẹ́wọ̀n, ó yẹra lọ sí Galili.
13. Lẹ́yìn tí ó kúrò ní Nasarẹti, ó ń lọ gbè Kapanaumu tí ó wà lẹ́bàá òkun ní agbègbè Sebuluni ati Nafutali.
14. Èyí rí bẹ́ẹ̀ kí ọ̀rọ̀ tí wolii Aisaya sọ lè ṣẹ pé:
15. “Ilẹ̀ Sebuluni ati ilẹ̀ Nafutali,ní ọ̀nà òkun,ní òdìkejì Jọdani,Galili àwọn àjèjì.
16. Àwọn eniyan tí ó jókòó ní òkùnkùnrí ìmọ́lẹ̀ ńlá.Ìmọ́lẹ̀ mọ́ sórí àwọn tí ó jókòóní ilẹ̀ tí òjìji ikú wà.”
17. Láti àkókò yìí ni Jesu ti bẹ̀rẹ̀ sí waasu pé, “Ẹ ronupiwada, nítorí ìjọba ọ̀run súnmọ́ ìtòsí.”