17. Èyí ṣẹlẹ̀ kí ọ̀rọ̀ tí wolii Jeremaya sọ lè ṣẹ pé,
18. “A gbọ́ ohùn kan ní Rama,ẹkún ati ọ̀fọ̀ gidi.Rakẹli ń sunkún nítorí àwọn ọmọ rẹ̀;ó kọ̀, kò gba ìpẹ̀,nítorí wọn kò sí mọ́.”
19. Lẹ́yìn tí Hẹrọdu ti kú, angẹli Oluwa kan fara han Josẹfu ní ojú àlá ní Ijipti.
20. Ó sọ fún un pé, “Dìde, gbé ọmọ náà ati ìyá rẹ́, kí o pada lọ sí ilẹ̀ Israẹli, nítorí àwọn tí wọ́n fẹ́ pa ọmọ náà ti kú.”
21. Josẹfu bá dìde, ó gbé ọmọ náà ati ìyá rẹ̀ pada sí ilẹ̀ Israẹli.