Kronika Kinni 12:6-11 BIBELI MIMỌ (BM)

6. Elikana, Iṣaya, ati Asareli, Joeseri, ati Jaṣobeamu, láti inú ìdílé Kora,

7. Joela, ati Sebadaya, àwọn ọmọ Jehoramu, ará Gedori.

8. Àwọn ọkunrin tí wọ́n wá láti inú ẹ̀yà Gadi láti darapọ̀ mọ́ Dafidi, ní ibi ààbò tí ó wà ninu aṣálẹ̀ nìwọ̀nyí; akọni ati ògbólógbòó jagunjagun ni wọ́n, wọ́n já fáfá ninu lílo apata ati ọ̀kọ̀, ojú wọn dàbí ti kinniun, ẹsẹ̀ wọn sì yá nílẹ̀ bíi ti ẹsẹ̀ àgbọ̀nrín lórí òkè.

9. Orúkọ wọn, ati bí wọ́n ṣe tẹ̀léra nìyí: Eseri ni olórí wọn, lẹ́yìn náà ni Ọbadaya, Eliabu;

10. Miṣimana, Jeremaya,

11. Atai, Elieli,

Kronika Kinni 12