7. Nígbà tí ẹ̀mí mi ń bọ́ lọ,mo gbadura sí ìwọ OLUWA,o sì gbọ́ adura mi ninu tẹmpili mímọ́ rẹ.
8. Àwọn tí wọn ń sin àwọn oriṣa lásánlàsàn kọ̀,wọn kò pa ìlérí wọn sí ọ mọ́.
9. Ṣugbọn n óo rúbọ sí ọ pẹlu ohùn ọpẹ́,n óo sì san ẹ̀jẹ́ mi.Ti OLUWA ni ìgbàlà!”
10. OLUWA bá pàṣẹ fún ẹja tí ó gbé Jona mì, ó sì lọ pọ̀ ọ́ sí èbúté, lórí ilẹ̀ gbígbẹ.