Joẹli 3:18-21 BIBELI MIMỌ (BM)

18. “Nígbà náà, àwọn òkè ńlá yóo kún fún èso àjàrà,agbo mààlúù yóo sì pọ̀ lórí àwọn òkè kéékèèké.Gbogbo àwọn odò Juda yóo kún fún omi.Odò kan yóo bẹ̀rẹ̀ sí ṣàn láti ilé OLUWA,yóo sì bomi rin àfonífojì Ṣitimu.

19. “Ijipti yóo di aṣálẹ̀;Edomu yóo sì di ẹgàn,nítorí ìwà ipá tí wọ́n hù sí àwọn ará Juda,nítorí wọ́n ti pa àwọn aláìṣẹ̀ ní ilẹ̀ wọn.

20. Ṣugbọn àwọn eniyan yóo máa gbé ilẹ̀ Juda títí lae,wọn óo sì máa gbé ìlú Jerusalẹmu láti ìrandíran.

21. N óo gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ àwọn tí ẹ pa, n kò sì ní dá ẹlẹ́bi sí,nítorí èmi OLUWA ni mò ń gbé Sioni.”

Joẹli 3