1. “Wò ó! Nígbà tó bá yá, tí mo bá dá ire Juda ati ti Jerusalẹmu pada,
2. n óo kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí àfonífojì Jehoṣafati,n óo sì dá wọn lẹ́jọ́ níbẹ̀;nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli, àwọn eniyan mi.Wọ́n ti fọ́n wọn káàkiri sí ààrin àwọn orílẹ̀-èdè,wọ́n sì ti pín ilẹ̀ mi.