Jobu 32:5-11 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Ṣugbọn nígbà tí Elihu rí i pé àwọn mẹtẹẹta kò lè fún Jobu lésì mọ́, inú bí i.

6. Ó ní,“Àgbàlagbà ni yín, ọmọde sì ni mí,nítorí náà ni ojú fi ń tì mí,tí ẹ̀rù sì ń bà mí láti sọ èrò ọkàn mi.

7. Mo ní kí ẹ̀yin àgbà sọ̀rọ̀,kí ọ̀rọ̀ yín sì fa ọgbọ́n yọ gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ orí yín.

8. Ṣugbọn ẹ̀mí tí ó wà ninu eniyan,tíí ṣe èémí Olodumare,ni ó ń fún eniyan ní ìmọ̀.

9. Kì í ṣe àwọn àgbà nìkan ni wọ́n gbọ́n,tabi pé arúgbó nìkan ni ó mọ òye ohun tó tọ́, tó yẹ.

10. Nítorí náà, ‘Ẹ fetí sílẹ̀,kí èmi náà lè sọ èrò ọkàn mi.’

11. “Mo farabalẹ̀ nígbà tí ẹ̀yin ń sọ̀rọ̀,mo fetí sí ọ̀rọ̀ ọgbọ́n yín,nígbà tí ẹ̀ ń ronú ohun tí ẹ fẹ́ sọ,

Jobu 32