Jobu 30:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. “Ṣugbọn nisinsinyii àwọn tí wọ́n kéré sí mi ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà,àwọn tí baba wọn kò tó fi wé àwọn ajátí ń ṣọ́ agbo ẹran mi.

2. Kí ni anfaani agbára wọn fún mi,àwọn tí wọn kò lókun ninu?

3. Ninu ìyà ati ebi,wọ́n ń jẹ gbòǹgbò igi gbígbẹ káàkiri lálẹ́ ninu aṣálẹ̀.

4. Ewé igi inú igbó ni wọ́n ń já jẹ,àní, àwọn igi ọwọ̀ tí kò ládùn kankan.

Jobu 30