Jobu 29:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Jobu tún ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ báyìí pé,

2. “Ìbá jẹ́ tún rí fún mi, bí ìgbà àtijọ́,nígbà tí Ọlọrun ń tọ́jú mi;

3. nígbà tí ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ń tàn sí mi lórí,tí mo kọjá ninu òkùnkùn pẹlu ìmọ́lẹ̀ rẹ̀;

4. kí ó tún rí fún mi bí ìgbà tí ara dẹ̀ mí,nígbà tí ìrẹ́pọ̀ wà láàrin Ọlọrun ati ìdílé mi;

Jobu 29