Jobu 15:2-9 BIBELI MIMỌ (BM)

2. “Ṣé ọlọ́gbọ́n a máa fọ èsì tí kò mọ́gbọ́n lọ́wọ́?Kí ó dàbí àgbá òfìfo?

3. Kí ó máa jiyàn lórí ọ̀rọ̀ tí kò wúlò,tabi ọ̀rọ̀ tí kò níláárí?

4. Ṣugbọn ò ń kọ ìbẹ̀rù Ọlọrun sílẹ̀,o sì ń dènà adura níwájú rẹ̀.

5. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ni ó ń fa irú ọ̀rọ̀ tí ń ti ẹnu rẹ jáde,ètè rẹ sì kún fún àrékérekè.

6. Ẹnu rẹ ni ó dá ọ lẹ́bi, kì í ṣe èmi;ẹ̀rí tí ò ń jẹ́ nípa rẹ ní ń ta kò ọ́.

7. “Ṣé ìwọ ni ẹni kinni tí wọ́n kọ́ bí láyé?Tabi o ṣàgbà àwọn òkè?

8. Ṣé o wà ninu ìgbìmọ̀ Ọlọrun?Tabi ìwọ nìkan ni o rò pé o gbọ́n?

9. Kí ni o mọ̀, tí àwa náà kò mọ̀?Òye kí ni o ní, tí ó jẹ́ ohun ìpamọ́ fún àwa?

Jobu 15