Jeremaya 51:1-3 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA ní,“Wò ó! N óo gbé ẹ̀mí apanirun kan dìde sí Babiloni,ati sí àwọn ará Kalidea;

2. n óo rán ìjì líle kan sí Babiloni,ìjì náà yóo fẹ́ ẹ dànù bí ìyàngbò ọkàyóo sì sọ ilẹ̀ rẹ̀ di ahoro,nígbà tí wọ́n bá gbógun tì í yípo, ní ọjọ́ ìpọ́njú.

3. Kí tafàtafà má kẹ́ ọrun rẹ̀,kí ó má sì gbé ẹ̀wù irin rẹ̀ wọ̀.Má ṣe dá àwọn ọdọmọkunrin rẹ̀ sí,pa gbogbo àwọn ọmọ ogun rẹ̀ run patapata.

Jeremaya 51