Jeremaya 48:40-43 BIBELI MIMỌ (BM)

40. OLUWA ní,“Wò ó, ẹnìkan yóo fò wá bí ẹyẹ idì,yóo sì na ìyẹ́ apá rẹ̀ lé Moabu lórí.

41. Ogun yóo kó àwọn ìlú Moabu,wọn óo sì gba àwọn ibi ààbò rẹ̀.Ní ọjọ́ náà, ọkàn àwọn ọmọ ogun Moabu yóo dàbí ọkàn obinrin tí ó ń rọbí,

42. Moabu yóo parun, kò ní jẹ́ orílẹ̀-èdè mọ́,nítorí pé ó ṣe ìgbéraga sí OLÚWA.

43. Ẹ̀yin ará Moabu,ìpayà, ọ̀gbun ati tàkúté ń bẹ níwájú yín!

Jeremaya 48