Jeremaya 31:8-12 BIBELI MIMỌ (BM)

8. Ẹ wò ó! N óo kó wọn wá láti ilẹ̀ àríwá,n óo kó wọn jọ láti òpin ayé.Àwọn afọ́jú ati arọ yóo wà láàrin wọn,ati aboyún ati àwọn tí wọn ń rọbí lọ́wọ́.Ogunlọ́gọ̀ eniyan ni àwọn tí yóo pada wá síbí.

9. Tẹkúntẹkún ni wọn yóo wá,tàánútàánú ni n óo sì fi darí wọn pada.N óo mú kí wọn rìn ní etí odò tí ń ṣàn,lójú ọ̀nà tààrà, níbi tí wọn kò ti ní fẹsẹ̀ kọ;nítorí pé baba ni mo jẹ́ fún Israẹli, àkọ́bí mi sì ni Efuraimu.”

10. OLUWA ní, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ èmi OLUWA, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè,kí ẹ sì kéde rẹ̀ ní èbúté lókèèrè réré;ẹ sọ pé, ‘Ẹni tí ó fọ́n Israẹli ká ni yóo kó wọn jọ,yóo sì máa tọ́jú wọn, bí olùṣọ́-aguntan tíí tọ́jú agbo aguntan rẹ̀.’

11. Nítorí OLUWA yóo ra ilé Jakọbu pada,yóo rà wọ́n pada lọ́wọ́ ẹni tí ó lágbára jù wọ́n lọ.

12. Wọn yóo wá kọrin lórí òkè Sioni,wọn óo sì yọ̀ lórí nǹkan ọ̀pọ̀ oore tí OLUWA yóo ṣe fún wọn:Wọ́n óo yọ̀ nítorí oore ọkà ati waini ati òróró,ati aguntan ati ẹgbọ̀rọ̀ mààlúù;ayé wọn óo dàbí ọgbà tí à ń bomi rin, wọn kò ní dààmú mọ́.

Jeremaya 31