Jeremaya 31:1-5 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA ní, “Àkókò ń bọ̀ tí n óo jẹ́ Ọlọrun gbogbo ìdílé Israẹli,tí àwọn náà yóo sì jẹ́ eniyan mi.

2. Àwọn tí wọ́n bọ́ lọ́wọ́ idà, rí àánú OLUWA ninu aṣálẹ̀;nígbà tí Israẹli ń wá ìsinmi,

3. OLUWA yọ sí wọn láti òkèèrè.Ìfẹ́ àìlópin ni mo ní sí ọ,nítorí náà n kò ní yé máa fi òtítọ́ bá ọ lò.

4. N óo tún yín gbé dìde, ẹ óo sì di ọ̀tun, ẹ̀yin ọmọ Israẹli.Ẹ óo tún fi aro lu ìlù ayọ̀, ẹ óo sì jó ijó ìdùnnú.

5. Ẹ óo tún ṣe ọgbà àjàrà sórí òkè Samaria;àwọn tí wọ́n gbin àjàrà ni yóo sì gbádùn èso orí rẹ̀.

Jeremaya 31