35. sibẹ ẹ̀ ń sọ pé, ‘Ọwọ́ wa mọ́;dájúdájú, OLUWA ti dá ọwọ́ ibinu rẹ̀ dúró lára wa.’Ẹ wò ó! N óo dá yín lẹ́jọ́,nítorí ẹ̀ ń sọ pé ẹ kò dẹ́ṣẹ̀.
36. Ẹ̀ ń fi ara yín wọ́lẹ̀ káàkiri;ẹ̀ ń yà síhìn-ín sọ́hùn-ún!Bí Asiria ti dójú tì yín,bẹ́ẹ̀ ni Ijipti náà yóo dójú tì yín.
37. Ẹ óo ká ọwọ́ lérí ninígbà tí ẹ óo bá jáde níbẹ̀.Nítorí OLUWA ti kọ àwọn tí ẹ gbójúlé,wọn kò sì ní ṣe yín níre.”