Jeremaya 12:5-8 BIBELI MIMỌ (BM)

5. OLUWA ní,“Bí o bá àwọn tí ń fi ẹsẹ̀ sáré sáré, tí ó bá rẹ̀ ọ́,báwo ni o ṣe lè bá ẹṣin sáré?Bí o bá sì ń ṣubú ní ilẹ̀ tí ó tẹ́jú,báwo ni o óo ti ṣe nígbà tí o bá dé aṣálẹ̀ Jọdani?

6. Nítorí pé àwọn arakunrin rẹ pàápàáati àwọn ará ilé baba rẹti hu ìwà ọ̀dàlẹ̀ sí ọ;àwọn gan-an ni wọ́n ń ṣe èké rẹ:Má gbẹ́kẹ̀lé wọn,bí wọ́n bá tilẹ̀ ń sọ̀rọ̀ rere sí ọ.”

7. OLUWA wí pé,“Mo ti kọ ilé mi sílẹ̀;mo ti kọ ogún tí a pín fún mi sílẹ̀.Mo ti fa ẹni tí ọkàn mi ń fẹ́ lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.

8. Ogún mi ti dàbí kinniun inú igbó sí mi,ó ti sọ̀rọ̀ burúkú sí mi;nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.

Jeremaya 12