Jẹnẹsisi 27:24-29 BIBELI MIMỌ (BM)

24. Ó bèèrè pé, “Ṣé ìwọ gan-an ni Esau, ọmọ mi?” Jakọbu bá dáhùn pé, “Èmi ni.”

25. Nígbà náà ni ó wí pé, “Gbé oúnjẹ náà súnmọ́ mi, kí n jẹ ninu ẹran tí ọmọ mi pa, kí n sì súre fún ọ.” Jakọbu bá gbé oúnjẹ náà súnmọ́ ọn, ó jẹ ẹ́, ó bu ọtí waini fún un, ó sì mu ún.

26. Isaaki baba rẹ̀ bá pè é ó ní, “Súnmọ́ mi, ọmọ mi, kí o sì fi ẹnu kò mí lẹ́nu.”

27. Jakọbu bá súnmọ́ baba rẹ̀, ó fi ẹnu kò ó lẹ́nu. Baba rẹ̀ gbóòórùn aṣọ rẹ̀, ó sì súre fún un, ó ní,“Òórùn ọmọ mi dàbí òórùn oko tí OLUWA ti bukun.

28. Kí Ọlọrun fún ọ ninu ìrì ọ̀runati ilẹ̀ tí ó dáraati ọpọlọpọ ọkà ati ọtí waini.

29. Kí àwọn eniyan máa sìn ọ́, kí àwọn orílẹ̀-èdè sì máa tẹríba fún ọ.Ìwọ ni o óo máa ṣe olórí àwọn arakunrin rẹ,àwọn ọmọ ìyá rẹ yóo sì máa tẹríba fún ọ.Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣépè lé ọ, òun ni èpè yóo mọ́,ẹnikẹ́ni tí ó bá sì súre fún ọ, ìre yóo mọ́ ọn.”

Jẹnẹsisi 27