Ìwé Òwe 29:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ẹni tí à ń báwí tí ó ń ṣoríkunkun,yóo parun lójijì láìsí àtúnṣe.

2. Nígbà tí olódodo bá di eniyan pataki,àwọn eniyan a máa yọ̀,ṣugbọn nígbà tí eniyan burúkú bá wà lórí oyè,àwọn eniyan a máa kérora.

3. Ọlọ́gbọ́n ọmọ a máa mú inú baba rẹ̀ dùn,ṣugbọn ẹni tí ń tẹ̀lé aṣẹ́wó kiri, ń fi ọrọ̀ ara rẹ̀ ṣòfò.

4. Ọba tí ó bá ń ṣe ìdájọ́ òdodo, a máa fìdí orílẹ̀-èdè múlẹ̀,ṣugbọn ọba onírìbá a máa dojú orílẹ̀-èdè bolẹ̀.

5. Ẹni tí ó bá ń pọ́n aládùúgbò rẹ̀,ń dẹ àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ̀.

6. Eniyan burúkú bọ́ sinu àwọ̀n ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,ṣugbọn olódodo lè kọrin, ó sì lè máa yọ̀.

Ìwé Òwe 29