Isikiẹli 21:6-12 BIBELI MIMỌ (BM)

6. “Ìwọ ọmọ eniyan, máa mí ìmí ẹ̀dùn, bí ẹni tí ọkàn rẹ̀ ti dàrú, tí ó sì ń kẹ́dùn níwájú wọn.

7. Bí wọ́n bá bi ọ́ pé kí ló dé tí o fi ń mí ìmí ẹ̀dùn, sọ fún wọn pé nítorí ìròyìn tí o gbọ́ ni. Nígbà tí ó bá ṣẹlẹ̀, ọkàn gbogbo eniyan yóo dàrú, ọwọ́ wọn yóo rọ ìrẹ̀wẹ̀sì yóo dé bá wọn, ẹsẹ̀ wọn kò ní ranlẹ̀ mọ́. Wò ó! Yóo ṣẹlẹ̀ bẹ́ẹ̀, n óo sì mú un ṣẹ. Èmi OLUWA Ọlọrun ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”

8. OLUWA tún bá mi sọ̀rọ̀, ó ní,

9. “Ìwọ ọmọ eniyan, sọ àsọtẹ́lẹ̀ pé èmi: OLUWA Ọlọrun ní:Ẹ wo idà, àní idà tí a ti pọ́n, tí a sì ti fi epo pa.

10. A ti pọ́n ọn láti fi paniyan;a ti fi epo pa á, kí ó lè máa kọ mànà bíi mànàmáná.Ọ̀rọ̀ yìí kìí ṣe ọ̀rọ̀ àríyá;nítorí àwọn eniyan mi kọ̀, wọn kò náání ìkìlọ̀ ati ìbáwí mi.

11. Nítorí náà, a pọ́n idà náà, a sì fi epo pa á,kí á lè fi lé ẹni tí yóo fi paniyan lọ́wọ́.

12. Ìwọ ọmọ eniyan, kígbe, kí o sì pohùnréré ẹkún,nítorí àwọn eniyan mi ni a yọ idà sí;ati àwọn olórí ní Israẹli.Gbogbo wọn ni a óo fi idà pa pẹlu àwọn eniyan mi.Nítorí náà káwọ́ lérí kí o sì máa hu.

Isikiẹli 21