Hosia 14:3-6 BIBELI MIMỌ (BM)

3. Asiria kò lè gbà wá là, bẹ́ẹ̀ ni a kò ní gun ẹṣin; a kò sì ní pe oriṣa, tíí ṣe iṣẹ́ ọwọ́ wa, ní Ọlọrun wa mọ́. OLUWA, ìwọ ni ò ń ṣàánú fún ọmọ tí kò lẹ́nìkan.”

4. Ọlọrun ní,“N óo gba ìwà aiṣootọ lọ́wọ́ wọn,n óo fẹ́ wọn tọkàntọkàn,nítorí n kò bínú sí wọn mọ́.

5. Bí ìrì ni n óo máa sẹ̀ sí Israẹli,ẹwà rẹ̀ yóo yọ bí òdòdó lílì,gbòǹgbò rẹ̀ yóo sì múlẹ̀ bíi gbòǹgbò igi kedari Lẹbanoni.

6. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ yóo tàn kálẹ̀;ẹwà rẹ̀ yóo yọ bíi ti igi olifi,òórùn rẹ̀ yóo sì dàbí ti igi Lẹbanoni.

Hosia 14