32. Bí ó tilẹ̀ mú kí ìbànújẹ́ dé bá wa,yóo ṣàánú wa, yóo tù wá ninu,gẹ́gẹ́ bí ọpọlọpọ ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.
33. Nítorí pé kì í kàn déédé ni eniyan láratabi kí ó mú ìbànújẹ́ dé bá eniyan láìní ìdí.
34. OLUWA kò faramọ́ pé kí á máa ni àwọn ẹlẹ́wọ̀n lára lórí ilẹ̀ ayé,
35. kí á máa já ẹ̀tọ́ olódodo gbà lọ́wọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá Ògo,
36. tabi kí á du eniyan ní ìdájọ́ òdodo.
37. Ta ló pàṣẹ nǹkankan rí tí ó sì rí bẹ́ẹ̀,láìjẹ́ pé OLUWA ló fi ọwọ́ sí i?
38. Àbí kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá Ògoni rere ati burúkú ti ń jáde?
39. Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè kan yóo fi máa ráhùnnígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40. Ẹ jẹ́ kí á yẹ ara wa wò,kí á tún ọ̀nà wa ṣe,kí á sì yipada sí ọ̀dọ̀ OLUWA.
41. Ẹ jẹ́ kí á gbé ojú wa sókè,kí á ra ọwọ́ ẹ̀bẹ̀ sí Ọlọrun ọ̀run:
42. “A ti ṣẹ̀, a sì ti ṣoríkunkun,ìwọ OLUWA kò sì tíì dáríjì wá.
43. “O gbé ibinu wọ̀ bí ẹ̀wù,ò ń lépa wa,o sì ń pa wá láì ṣàánú wa.
44. O ti fi ìkùukùu bo ara rẹ,tóbẹ́ẹ̀ tí adura kankan kò lè kọjá sọ́dọ̀ rẹ.
45. O ti sọ wá di ààtànati ohun ẹ̀gbin láàrin àwọn eniyan.
46. “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ń wẹnu sí wa lára.