Ẹkún Jeremaya 3:29-34 BIBELI MIMỌ (BM)

29. Kí ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀ tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀,bóyá ìrètí lè tún wà fún un.

30. Kí ó kọ etí rẹ̀ sí ẹni tí ó fẹ́ gbá a létí,kí wọ́n sì fi àbùkù kàn án.

31. Nítorí OLUWA kò ní ta wá nù títí lae.

32. Bí ó tilẹ̀ mú kí ìbànújẹ́ dé bá wa,yóo ṣàánú wa, yóo tù wá ninu,gẹ́gẹ́ bí ọpọlọpọ ìfẹ́ rẹ̀ tí kì í yẹ̀.

33. Nítorí pé kì í kàn déédé ni eniyan láratabi kí ó mú ìbànújẹ́ dé bá eniyan láìní ìdí.

34. OLUWA kò faramọ́ pé kí á máa ni àwọn ẹlẹ́wọ̀n lára lórí ilẹ̀ ayé,

Ẹkún Jeremaya 3