Diutaronomi 5:1-4 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Mose pe gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ, ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ọmọ Israẹli, ẹ gbọ́ àwọn ìlànà ati àwọn òfin tí n óo kà fun yín lónìí; ẹ kọ́ wọn, kí ẹ sì rí i pé ẹ̀ ń tẹ̀lé wọn.

2. OLUWA Ọlọrun wa bá wa dá majẹmu kan ní òkè Horebu.

3. Kì í ṣe àwọn baba wa ni OLUWA bá dá majẹmu yìí, ṣugbọn àwa gan-an tí a wà láàyè níhìn-ín lónìí ni ó bá dá majẹmu náà.

4. OLUWA bá yín sọ̀rọ̀ lojukooju lórí òkè ní ààrin iná.

Diutaronomi 5