Aisaya 56:8-12 BIBELI MIMỌ (BM)

8. OLUWA Ọlọrun tí ń kó àwọn tí ogun túká ní Israẹli jọ sọ pé,“N óo tún kó àwọn mìíràn jọ,kún àwọn tí mo ti kọ́ kó jọ.”

9. Gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè láti òkèèrè, ẹ máa bọ̀,gbogbo yín ẹ máa bọ̀ bí ẹranko inú ìgbẹ́, ẹ wá jẹ àjẹrun.

10. Afọ́jú ni àwọn aṣọ́de Israẹligbogbo wọn kò mọ nǹkankan.Ajá tí ó yadi ni wọ́n,wọn kò lè gbó;oorun ni wọ́n fẹ́ràn.Wọn á dùbúlẹ̀, wọn á máa lá àlá.

11. Wọ̀bìà ni wọ́n, alájẹkì,wọn kì í yó.Àwọn olùdarí wọn pàápàá kò mọ nǹkankan.Gbogbo wọn ti tẹ̀ sí ọ̀nà ara wọn,olukuluku wọn ń wá èrè fún ara rẹ̀.

12. Wọn á máa sọ pé: “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á mu waini,ẹ jẹ́ kí á mu ọtí líle ní àmuyó,bí òní ṣe rí ni ọ̀la yóo rí, yóo dùn tayọ.”

Aisaya 56