Aisaya 26:12-15 BIBELI MIMỌ (BM)

12. OLUWA ìwọ yóo fún wa ní alaafia,nítorí pé ìwọ ni o ṣe gbogbo iṣẹ́ wa fún wa.

13. OLUWA, Ọlọrun wa,àwọn oluwa mìíràn ti jọba lórí waṣugbọn orúkọ rẹ nìkan ni àwa mọ̀.

14. Wọ́n ti kú, wọn kò ní wà láàyè mọ́,ẹ̀mí wọn kò ní dìde mọ́ ní isà òkú.Nítorí bẹ́ẹ̀ ni o ṣe jẹ wọ́n níyà,o sì pa wọ́n run,o sì ti sọ gbogbo ìrántí wọn di ohun ìgbàgbé.

15. Ṣugbọn ìwọ OLUWA ti mú kí orílẹ̀-èdè náà pọ̀ sí i,OLUWA, o ti bukun orílẹ̀-èdè náà,gbogbo ààlà ilẹ̀ náà ni o ti bì sẹ́yìn,o sì ti buyì kún ara rẹ.

Aisaya 26