Sekaráyà 2:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ikogun fún iránṣẹ́ wọn: ẹ̀yín yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.

10. “Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Síónì: Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárin rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.

11. “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi: èmi yóò sì gbé àárin rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.

12. Olúwa yóò sì jogún Júdà ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jérúsálẹ́mù.

13. Ẹ̀ dákẹ̀, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”

Sekaráyà 2