Sáàmù 69:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Gbàmí, Ọlọ́run,nítorí omi tí kún dé ọrùn mi.

2. Mo ń rì nínú ìrà jínjìn,níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé.Mo ti wá sínú omi jínjìn;ìkún omi bò mí mólẹ̀.

3. Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́;ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú,nígbà ti èmi dúró de Ọlọ́run mi

4. Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìíwọn ju irun orí mi; lọpúpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí,àwọn tí ń wá láti pa mí runA fi ipá mú miláti san ohun tí èmi kò jí.

5. Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run;ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú Rẹ.

6. Má ṣe dójú tì àwọn tí ó ní ìrètí nínú Rẹnítorí mi, Olúwa, Ọlọ́run àwọn ọmọ ogun;Má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi,Ọlọ́run Ísírẹ́lì.

7. Nítorí Rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn,ìtìjú sì bo ojú mi.

8. Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi;àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;

Sáàmù 69