Òwe 27:10-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Má ṣe kọ ọ̀rẹ́ rẹ àti ọ̀rẹ́ baba rẹ sílẹ̀,má sì ṣe lọ sílé arákùnrin rẹ nígbà tí ìdàámú dé bá ọó sàn kí o jẹ́ aládúúgbò tí ó súnmọ́ ni ju arákùnrin tí ó jìnnà síni.

11. Gbọ́n, ọmọ mi, kí o sì mú ayọ̀ wá sínú ọkàn minígbà náà ni mo le dá gbogbo ẹni tí ó bá kẹ́gàn mi.

12. Ọlọ́gbọ́n rí ewu, ó sì fara pamọ́ṣùgbọ́n aláìgbọ́n rí kàkàkí ó dúró ó tẹ̀ṣíwájú, ó sì jìyà rẹ̀.

13. Gba aṣọ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àjòjìfi ṣe ẹ̀rí ìdúró bí o bá ṣe onídùúró fún obìnrin oní ìṣekúṣe.

14. Bí ènìyàn kan ń kígbe e ṣúre fún aládùúgbò rẹ ní òwúrọ̀a ó kà á sí bí èpè.

15. Àyà tí ó máa ń jà dàbíọ̀wààrà òjò ní ọjọ́ tí òjò ń rọ̀;

16. dídá a lẹ́kun dàbí ìgbà tí ènìyàn ń dá afẹ́fẹ́ lẹ́kuntàbí bí ẹni tí ó gbá òróró.

17. Bí irin tí ń pọ́n irin múbẹ́ẹ̀ ni ènìyàn kan ń pọ́n ẹlòmíràn mú.

Òwe 27