Òwe 23:14-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Bí ìwọ fi pàṣán nà án,ìwọ ó sì gbà ọkàn rẹ̀ là kúrò ní ọ̀run-àpáàdì.

15. Ọmọ mi, bí ọkàn rẹ bá gbọ́n,ọkàn mi yóò yọ̀, àní èmi pẹ̀lú.

16. Inú mi yóò sì dùn nígbà tí ètè rẹ̀ bá ń sọ̀rọ̀ títọ́.

17. Má ṣe jẹ́ kí àyà rẹ ó ṣe ìlara sí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,ṣùgbọ́n kí ìwọ ó wà ní ìbẹ̀rù Olúwa,ní ọjọ́ gbogbo.

18. Nítorí pé ìkẹyìn ń bẹ nítòótọ́;ìrètí rẹ̀ kì yóò sì gé kúrò.

19. Gbọ́, ìwọ ọmọ mi, kí o sì gbọ́n,kí o sì máa tọ́ àyà rẹ sí ọ̀nà títọ́.

20. Má ṣe wà nínú àwọn ọ̀mùtí;àti àwọn wọ̀bìà alájẹkì ọ̀jẹun;

21. Nítorí pé ọ̀mùtí àti ọ̀jẹun ni yóò di talákà;ìmúni-tòògbé ní sì ń fi àkísà wọ ọkùnrin láṣọ.

22. Fetí sí ti baba rẹ tí ó bí ọ,má sì ṣe gan ìyá rẹ, nígbà tí o bá gbó

Òwe 23