Òwe 22:18-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ;nígbà tí a sì pèṣè wọn tán ní ètè rẹ.

19. Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà níti Olúwa,èmi fi hàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.

20. Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradárasí ọ níti ìmọ̀ràn àti níti ẹ̀kọ́,

21. Kí ó lè mú ọ mọ dídájú ọ̀rọ̀ òtítọ́;kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?

22. Má ṣe ja talákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ talákà:bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè:

23. Nítorí Olúwa yóò gbéjà wọn,yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.

24. Má ṣe bá oníbìínu ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́;má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.

25. Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀,ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.

Òwe 22