7. Olódodo ènìyàn a máa gbé ìgbé ayé àìlábùkùìbùkún ni fún àwọn ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.
8. Nígbà tí ọba bá jókóò sórí ilẹ̀ rẹ̀ láti ṣe ìdájọ́yóò fẹ́ gbogbo ibi dànù pẹ̀lú ojú rẹ̀.
9. Táni ó le è wí pé, “Mo ti ṣe ọkàn mi ní mímọ́,mo mọ́, n kò sì lẹ́ṣẹ̀”?
10. Ìdíwọ̀n èké àti òṣùwọ̀n ìrẹ́jẹ Olúwa kórìíra méjèèjì.
11. Kódà a mọ ọmọdé nípa iṣẹ́ rẹ̀nípa pe bóyá iṣẹ́ rẹ mọ́ tàbí pé ó tọ̀nà.
12. Etí tí ó ń gbọ́ àti ojú tí ó ń ríran Olúwa ni ó dá méjèèjì.
13. Má ṣe fẹ́ràn oorun, àìṣe bẹ́ẹ̀ ìwọ yóò di talákàmá ṣe sùn ìwọ yóò sì ní oúnjẹ láti tún fi tọrọ.
14. “Kò dára, kò dára” ní ẹni tó ra ọjà máa ń wínígbà tí ó bá kúrò níbẹ̀ tán, yóò máayangàn bí òun tí ṣe rí i rà sí.
15. Góòlù wà, iyùn sì wà rẹpẹtẹṣùgbọ́n, ahọ́n tí ń sọ ìmọ̀ gan an ni ọ̀ṣọ́ iyebíye.
16. Gba abọ́ ẹni tí ó ṣe onídùúró fún àlejò;mú un lọ́wọ́ bí ìbúra bí ó bá ṣe é fún obìnrin onírìnkurìn.
17. Oúnjẹ tí a fi ọ̀nà ẹ̀rú rí máa ń dùn lẹ́nu ènìyànṣùgbọ́n, a yọrí sí bi ẹnu tí ó kún fún èèpẹ̀.
18. Pa ètè rẹ mọ́ nípa wíwá ìmọ̀rànbí o bá ń jagun, gba ìtọ́ṣọ́nà.
19. Olófòófó dalẹ̀ àsírínítorí náà yẹra fún ènìyàn tí ń rojọ́ jù.
20. Bí ènìyàn kan bá ṣépè fún baba tàbí ìyá rẹ̀,ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ni a ó pa kú nínú òkùnkùn biribiri.
21. Ogún tí a kó jọ kíákíá ní ìbẹ̀rẹ̀kì yóò ní ìbùkún ní ìgbẹ̀yìn gbẹ́yín.
22. Má ṣe wí pé, “N ó ṣẹ̀ṣan àṣìṣe rẹ yìí fún ọ”Dúró de Olúwa yóò sì gbà ọ́ là.
23. Olúwa kórìíra òdiwọ̀n èké.Òṣùwọ̀n ìrẹ́jẹ kò sì tẹ́ ẹ lọ́rùn.
24. Olúwa ni ó ń ṣe olùdarí ìgbésẹ̀ ènìyànBáwo wá ni òye gbogbo ọ̀nà ènìyàn ṣe le yé ni?