Òwe 13:15-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Òye pípé ń mú ni rí ojú rereṢùgbọ́n ọ̀nà aláìsòótọ́ kì í tọ́jọ́.

16. Gbogbo olóye ènìyàn máa ń hùwà pẹ̀lú ìmọ̀Ṣùgbọ́n aláìgbọ́n a fi ìwà òmùgọ̀ rẹ̀ hàn.

17. Ìránṣẹ́ búburú bọ́ sínú ìdàámúṣùgbọ́n aṣojú olóòtọ́ mú ìwòsàn wá.

18. Ẹni tí ó kọ ìbáwí yóò di talákà yóò sì rí ìtìjú,ṣùgbọ́n ẹni tí ó gbọ́ ìbáwí ni yóò rí ọlá.

19. Ìfẹ́ tí a múṣẹ dùnmọ́ ọkànṣùgbọ́n ìríra ni fún aṣiwèrè láti kúrò nínú ibi.

20. Ẹni tí ó ń bá ọlọ́gbọ́n rìn yóò gbọ́nṣùgbọ́n ẹni tí ń bá aláìgbọ́n kẹ́gbẹ́ ń pa ara rẹ̀ lára.

Òwe 13