Onídájọ́ 8:33-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Láìpẹ́ jọjọ lẹ́yìn ikú Gídíónì ni àwọn ará Ísírẹ́lì ṣe àgbérè tọ Báálì lẹ́yìn, wọ́n fi Báál-Beriti ṣe òrìṣà wọn.

34. Wọn kò sì rántí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀ta wọn gbogbo tí ó wà ní gbogbo àyíká wọn.

35. Wọ́n kùnà láti fi inú rere hàn sí ìdílé Jérú-Báálì (èyí ni Gídíónì) fún gbogbo ore tí ó ṣe fún wọn.

Onídájọ́ 8