Nọ́ḿbà 34:15-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún ti wọn ní ìhà Jódánì létí i Jéríkò, Gábásì, ní ìhà ìlà oòrùn.”

16. Olúwa sọ fún Mósè pé,

17. “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Élíásárì àlùfáà àti Jóṣúà ọmọ Núnì.

18. Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.

19. Èyí ni orúkọ wọn:Kálẹ́bù ọmọ Jéfúnè,láti ẹ̀yà Júdà;

20. Ṣémúélì ọmọ Ámíhúdì,láti ẹ̀yà Ṣíméónì;

21. Élídádì ọmọ Kísílónì,láti ẹ̀yà Bẹ́ńjámínì;

22. Búkì ọmọ Jógílì,láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dánì;

23. Háníélì ọmọ Éfódù,láti ẹ̀yà Mánásè, olórí àwọn ọmọ Jóṣẹ́fù,

24. Kémúélì ọmọ Ṣífílánì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Éfúráímù, ọmọ Jóṣẹ́fù;

25. Élísáfánì ọmọ Pánákì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Ṣébúlunì;

26. Pátíélì ọmọ Ásánì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Ísákárì;

27. Áhíhúdù ọmọ Ṣélómì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Áṣérì;

28. Pédàhẹ́lì ọmọ Ámíhúdì,olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Náfitalì.”

29. Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ilẹ̀ Kénánì.

Nọ́ḿbà 34