Nọ́ḿbà 31:31-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Nígbà náà Mósè àti Élíásárì àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti paláṣẹ fún Mósè.

32. Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n (675,000) ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.

33. Ẹgbàá mẹ́rìndínlógójì (72,000) màlúù

34. ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin (61,000) kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,

35. Pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, (32,000) ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.

36. Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́:ẹgbàá méjìdínláàdọ́san (337,500) ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.

37. Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n (675) àgùntàn;

38. ẹgbọ̀rọ̀ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, (36,000) tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàdọ́rin (72);

39. kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀dógún, ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, (30,500) tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta; (61).

40. Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ (16,000) ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n. (32)

Nọ́ḿbà 31