Nọ́ḿbà 26:15-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Àwọn ọmọ Gádì bí ìdílé wọn:ti Ṣéfónì, ìdílé Ṣéfónì;ti Hágígì, ìdílé Hágígì;ti Ṣúnì, ìdílé Ṣúnì;

16. ti Ósínì, ìdílé Ósíní;ti Érì, ìdílé Érì;

17. ti Árédì, ìdílé Árédì;ti Árólì, ìdílé Árólì.

18. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gádì tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (40,500).

19. Àwọn ọmọ Júdà ni Érì àti Ónánì, ṣùgbọ́n Érì àti Ónánì kú ní ilẹ̀ Kénánì.

20. Àti àwọn ọmọ Júdà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn:ti Ṣélà, ìdílé Ṣélà;ti Pérésì, ìdílé Pérésì;ti Sérà, ìdílé Ṣérà.

21. Àwọn ọmọ Pérésì:ti Hésírónì, ìdílé Hésírónì;ti Hámúlù, ìdílé Hámúlù.

22. Wọ̀nyí ni ìdílé Júdà; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. (76,500).

Nọ́ḿbà 26