Nọ́ḿbà 21:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Àmọ́ Ísírẹ́lì ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Ánónì lọ dé Jábókù, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ámónì, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.

25. Ísírẹ́lì sì gba gbogbo ìlú Ámórì wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Hésíbónì, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.

26. Hésíbónì ni ìlú Ṣíhónì ọba àwọn ará Ámórì, ẹni tí ó bá ọba ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Ánónì.

27. Ìdí nì yí tí akọrin sọ wí pé:“Wá sí Hésíbónì kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́;jẹ́ kí ìlú Ṣíhónì padà bọ̀ sípò.

28. “Iná jáde láti Hésíbónì,ọ̀wọ́ iná láti Ṣíhónì.Ó jó Árì àti Móábù run,àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Ánónì.

Nọ́ḿbà 21