26. Bọ́ aṣọ Árónì kí o sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Élíásárì, nítorí pé Árónì yóò kú ṣíbẹ̀.”
27. Mósè sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa láṣẹ: Wọ́n lọ sí orí òkè Hórì ní ojú gbogbo ìjọ ènìyàn.
28. Mósè bọ́ aṣọ Árónì ó sì gbe wọ ọmọ rẹ̀ Élíásárì, Árónì sì kú sí orí òkè. Nígbà náà Mósè àti Élíásárì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè,