1. Olúwa sọ fún Mósè àti Árónì pé:
2. “Èyí ni ohun tí òfin Olúwa pa láṣẹ béèrè lọ́wọ́ yín: Sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, kí wọn mú ẹgbọrọ ọ̀dọ́ màlúù pupa tí kò lábùkù tàbí àbàwọ́n, tí kò sì tí ì ru ẹrù rí.
3. Ẹ mú fún Élíásárì àlùfáà, yóò sì mu jáde lọ sí ẹ̀yìn ibùdó kí ó sì pa á ní ojú rẹ.
4. Nígbà náà ni Élíásárì àlùfáà yóò mú lára ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sórí ìka ọwọ́ rẹ̀ yóò sì wọn lẹ́ẹ̀méje ní ọ̀kánkán iwájú àgọ́ ìpàdé.