Nehemáyà 12:12-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Ní ìgbé ayé Jòíakímù, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà:ti ìdílé Ṣeráiáyà, Méráyà;ti ìdílé Jeremáyà, Hananíyà;

13. ti ìdílé Éṣírà, Mésúlámù;ti ìdílé Ámáráyà, Jéhóhánánì;

14. ti ìdílé Málúkì, Jònátanì;ti ìdílé Ṣékánáyà, Jóṣéfù;

15. ti ìdílé Hárímù, Ádíná;ti ìdílé Mérémótì Hélíkáyì;

16. ti ìdílé Ídò, Ṣekaráyà;ti ìdílé Gínétónì, Mésúlámù;

17. ti ìdílé Ábíjà, Ṣíkírì;ti ìdílé Míníámínì àti ti ìdílé Móádíà, Pílítaì;

18. ti ìdílé Bílígà, Ṣámúyà;ti ìdílé Ṣémáyà, Jéhónátanì;

19. ti ìdílé Jóíáríbù, Máténáyì;ti ìdílé Jédáíáyà, Húsì;

20. ti ìdílé Ṣálù, Káláyì;ti ìdílé Ámókì, Ébérì;

21. ti ìdílé Hílíkíáyà, Háṣábíáyà;ti ìdílé Jédáíáyà, Nétanẹ́lì.

22. Àwọn olóórí ìdílé àwọn ọmọ Léfì ní ìgbà ayé Élíáṣíbù, Jóíádà, Jóhánánì àti Jádúà, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dáríúsì ará a Páṣíà.

23. Àwọn olórí ìdílé láàrin àwọn ọmọ Léfì títí di àkókò Jóhánánì ọmọ Élíáṣíbù ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.

24. Àti àwọn olóórí àwọn ọmọ Léfì ni Háṣábáyà, Ṣérébáyà, Jéṣúà ọmọ Kádímíélì, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojúu wọn láti ròyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dáfídì ènìyàn Ọlọ́run.

Nehemáyà 12