Mátíù 18:5-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. “Àti pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ọmọ kékeré bí èyí nítorí orúkọ mi, gbà mí.

6. Ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni nínú yín tí ó bá mú ọ̀kan nínú àwọn ọmọkékeré wọ̀nyí tí ó gbà mí gbọ́ sìnà, yóò sàn fún un kí a so òkúta ńlá mọ́ ọn lọ́rùn, kí a sì rì í sí ìsàlẹ̀ ibú omi òkun.

7. “Ègbé ni fún ayé nítorí gbogbo ohun ìkọ̀sẹ̀ rẹ̀! Ohun ìkọ̀sẹ̀ kò le ṣe kó má wà, ṣùgbọ́n ègbé ni fún ọkùnrin náà nípaṣẹ̀ ẹni tí ìkọ̀sẹ̀ náà ti wá!

8. Nítorí náà, bí ọwọ́ tàbí ẹṣẹ̀ rẹ yóò bá mú ọ dẹ́ṣẹ̀, gé e kúrò, kí o sì jù ú nù. Ó kúkú sàn fún ọ láti wọ ìjọba ọ̀run ní akéwọ́ tàbí akésẹ̀ ju pé kí o ni ọwọ́ méjì àti ẹsẹ̀ méjì ki a sì sọ ọ́ sínú iná ayérayé.

Mátíù 18