Lúùkù 23:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Nígbà tí Pílátù gbọ́ orúkọ Gálílì, ó béèrè bí ọkùnrin náà bá jẹ́ ará Gálílì.

7. Nígbà tí ó sì mọ̀ pé ará ilẹ̀ Hẹ́rọ́dù ni, ó rán an sí Hẹ́rọ́dù, ẹni tí òun tìkárarẹ̀ wà ní Jerúsálémù ní àkókò náà.

8. Nígbà tí Hẹ́rọ́dù, sì rí Jésù, ó yọ̀ gidigidi; nítorí tí ó ti ń fẹ́ rí i pẹ ó sáà ti ń gbọ́ ìhìn púpọ̀ nítorí rẹ̀; ó sì ń retí láti rí i kí iṣẹ́ àmì díẹ̀ ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe.

9. Ó sì béèrè ọ̀rọ̀ púpọ̀ lọ́wọ́ rẹ̀; ṣùgbọ́n kò da a lóhùn rárá.

10. Àti àwọn olórí àlùfáà àti àwọn akọ̀wé dúró, wọ́n sì ń fí ẹ̀sùn kàn án gidigidi.

Lúùkù 23