Jóṣúà 4:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà tí gbogbo orílẹ̀-èdè náà kọjá nínú odò Jọ́dánì tan, Olúwa ṣọ fún Jóṣúà pé,

2. “Yan ọkùnrin méjìlá (12) nínú àwọn ènìyàn, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan,

3. kí o sì pàṣẹ fún wọn pé Ẹ gbé òkúta méjìlá (12) láti àárin odò Jọ́dánì ní ibi tí àwọn àlùfáà dúró sí, kí ẹ sì rù wọn kọjá, kí ẹ sì gbé wọn sí ibi tí ẹ̀yin yóò sùn ní alẹ́ yìí.”

4. Bẹ́ẹ̀ ni Jóṣúà pe àwọn ọkùnrin méjìlá (12) tí ó ti yàn nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ẹnìkan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kàn,

Jóṣúà 4