Jóòbù 24:14-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Panipani a dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́,a sì pa talákà àti aláìní, àti ní òru a di olè.

15. Ojú alágbèrè pẹ̀lú dúró deàfẹ̀mọ́júmọ́ ọjọ́; ‘Ó ní, ojúẹnìkan kì yóò rí mi;’ ó sì fi ìbòjú bojú rẹ̀.

16. Ní òkùnkùn wọn á rúnlẹ̀ wọlé,tí wọ́n ti fi ojú sọ fún ara wọnní ọ̀sán, wọn kò mọ̀ ìmọ́lẹ̀.

17. Nítorí pé bí òru dúdú ní òwúrọ̀fún gbogbo wọn; nítorí tí wọn sì mọ̀ ìbẹ̀rù òkùnkùn.

18. “Ó yára lọ bí ẹni lójú omi; ìpín wọn ní ilé ayé ni a ó parun;òun kò rìn mọ́ ní ọ̀nà ọgbà àjàrà.

19. Ọ̀dá àti òru ní ímú omi ojọ-didi gbẹ, bẹ́ẹ̀ní isà òkú írun àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀.

20. Inú ìbímọ yóò gbàgbé rẹ̀, kòkòròní yóò máa fi adùn jẹun lára rẹ̀,a kì yóò rántí ènìyàn búburúmọ́; Bẹ́ẹ̀ ní a ó sì ṣẹ ìwà búburú bí ẹní ṣẹ́ igi;

21. Ẹni tí o hù ìwà búburú sí àgàn tíkò ṣe rere sí opó.

22. Ṣùgbọ́n ó fi ipá Ọlọ́run rẹ̀ fà alágbáralọ pẹ̀lú; Ó dìde, kò sí ẹni tí ẹ̀mí rẹ̀ dá lójú.

23. Ọlọ́run sì fi ìwà àìléwu fún un,àti nínú èyí ní a ó sì tì i lẹ́yìn, ojúrẹ̀ sì wà ní ipa ọ̀nà wọn.

Jóòbù 24