24. Ọpọ́n rẹ̀ kún fún omi ọmú,egungun rẹ̀ sì tutù fún ọ̀rá.
25. Ẹlòmìíràn a sì kú ninú kíkoròọkàn rẹ̀, tí kò sì fi inú dídùn jẹun.
26. Wọ́n o dùbúlẹ̀ bákan náà nínúerùpẹ̀, kòkòrò yóò sì ṣùbò wọ́n.
27. “Kíyèsí i, èmi mọ̀ ìrò inú yín àtiàrékérekè ọkàn yín láti ṣe ìlòdì sí mi.
28. Nítorí tí ẹ̀yin wí pé, ‘Níbo ní iléọmọ aládé, àti níbo ní àgọ́àwọn ènìyàn búburú nì gbé wà?’
29. Ẹ̀yin kò béèrè lọ́wọ́ àwọn tí ń kọjálọ ní ọ̀nà? Ẹ̀yin kò mọ̀ àmì wọn, pé
30. Ènìyàn búburú ní a fi pamọ́ fúnọjọ́ ìparun? A ó sì mú wọnjáde ní ọjọ́ ríru ìbínú.
31. Ta ni yóò sọ ipa ọ̀nà rẹ̀ kò ó níojú, ta ni yóò sì san án padà fún un ní èyí tí ó ti ṣe?
32. Síbẹ̀ a ó sì sin ín ní ọ̀nà ipò òkú, a ósì máa ṣọ́ ibojì òkú.