Jóòbù 15:32-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

32. A ó mú un ṣẹ ṣáájú pípẹ́ ọjọ́ rẹ̀,ẹ̀ka rẹ̀ kì yóò sì tutù.

33. Yóò sì gbọ̀n àìpọ́n èṣo rẹ̀ dànù bí i àjàrà,yóò sì rẹ̀ ìyanna rẹ̀ nù bí i ti igi Ólífì.

34. Nítorí pé ayọ̀ àwọn àgàbàgebèyóò túká, iná ní yóò sì jó àgọ́ àwọn tí ó fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀.

35. Wọ́n lóyún ìwà ìkà, wọ́n sì bíẹ̀ṣẹ̀, ikùn wọn sì pèṣè ẹ̀tàn.”

Jóòbù 15